Àgbà òṣèré, Taiwo Hassan Ogogo ni àìsàn jẹjẹrẹ, a ń wá dókítà òyìnbó tàbí tí ìbílẹ̀ to le wò ó sàn - Àwọn ọmọ rẹ̀ figbe ta

Oríṣun àwòrán, Collage
Gbogbo ẹ̀dá lọ máa ń gbàdúrà fún ìlera pípé láti gbé ilé ayé àmọ́ bí àìsàn bá dé, yóò kó ìpayà àti ìbànújẹ de.
Gbajugbaja ọṣèré tíátà ni èdè Yorùbá, tí ọ̀pọ̀ èèyàn nifẹ rẹ, Taiwo Hassan, tí ọ̀pọ̀ èèyàn mọ̀ sí Ogogo lọ tí ń ṣàìsàn to lágbára báyìí.
Àìsàn náà sì lo ni ṣe pẹ̀lú àìsàn jẹjẹrẹ.
Ọmọ Ogogo lobinrin, Shakira Taiwo lo fi Ikede yii síta pẹ̀lú ẹkún ńlá nínú fídíò kan tó ṣe láti fi béèrè fún ìrànwọ́.
Fídíò náà sì lo gbé síta lójú òpó Instagram rẹ̀.
Gẹ́gẹ́ bí Shakira ṣe ń fi omijé ṣe àlàyé, ó ní àìsàn jẹjẹrẹ ọhun tí de ipele kẹrin.
"Ìdí sì nìyí tí àwọn dókítà ṣe sọ pé pé àwọn kò lè fún ní ìtọ́jú tí àwọn máa ń fún àwọn èèyàn tó bá ní àìsàn jẹjẹrẹ, tí a mọ̀ sí 'Chemotherapy' mọ."
Shakira Taiwo tẹsiwaju nínú ọ̀rọ̀ rẹ pé òun ko se fídíò náà láti fi tọrọ owo lọ́wọ́ ẹnikẹni.
O fikùn pé olùdíje sípò gomina lábẹ́ Asia ẹgbẹ́ òṣèlú APC nipinlẹ Ogun, Senatọ Solomon Adeola, tí ọ̀pọ̀ èèyàn mọ̀ sí Yayi, lo tí ń gbọ́ bukata ìnáwó lórí àìsàn baba òun.
O wa dúpẹ́ lọ́wọ́ àgbà oloselu náà fún ọwọ́ àànú to n na si Ogogo.
Shakira wá sísọ lójú rẹ pé "Mo ń wá àwọn onisegun to lè tojú baba mi bayi lọ́wọ́ àìsàn jẹjẹrẹ.
Bóyá àwọn onisegun oyinbo ni tàbí tí ìbílẹ̀.
Ẹ jọ̀ọ́ torí Ọlọ́run, bàbà mi kò fẹ́ kú, kò fẹ́ kú" Ọmọ Ogogo lọ ń fi ẹkún rawọ ẹ̀bẹ̀ sáwọn aráàlú náà."
Bákan náà ni Shakira ni inú ìrora ńlá ni bàbá òun wà báyìí, ẹnikẹ́ni tó bá sì lè wo àìsàn jẹjẹrẹ náà san, kí wọ́n kan sì òun tàbí àbúrò òun.
Bákan náà ni Shakira fi sita pé ó yẹ kí àgbà òṣèré náà tí lọ sí ilẹ̀ india fún ìtọ́jú àmọ́ kò le wọ bàálù torí àìsàn náà tí wọ ọ lára.

Oríṣun àwòrán, Kira_Taiwo/Instagram
A kò mọ pé Baba mi ni àìsàn jẹjẹrẹ, ọṣẹ kẹta rèé tí a mọ̀ - Haleemah Taiwo
Bákan náà ni ọmọbìnrin Ogogo miran, Haleemah Taiwo náà ṣe fídíò miran, tí òun náà ń fi omijé sọ̀rọ̀ láti béèrè ìrànwọ́ ọwọ́.
"Baba mi nifẹ lati gbe ile ayé, kò tètè mọ pe oun ni àìsàn jẹjẹrẹ àmọ́ ó ti tàn ka ara rẹ.
Ọ̀sẹ̀ mẹta sẹ́yìn rèé tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ mọ pe o ni àìsàn náà, táwọn dókítà sì lo tí kọjá ìtọ́jú.
A wá ń bẹ ẹnikẹ́ni to bá lè tojú rẹ, láti kan sì wà, a kò fẹ́ kí baba wá kú ó. "
Gbogbo àwọn ọṣèré tíátà bíi Toyin Abraham, Dayo Amusa àtàwọn míì sì lo n se alábàápín àwọn fídíò tí àwọn ọmọ Ogogo náà ṣe.
Wọn wá ń rọ àwọn onímọ̀ oyinbo àtàwọn onisegun ìbílẹ̀ to bá gbowọ, tí wọn lé wo àìsàn jẹjẹrẹ láti kan sì àwọn lórí aago.

Oríṣun àwòrán, Limataiwo_




























