Àjọ NEMA kéde agbègbè 37 tó wà nínú ewu ẹ̀kún omi, 15 l'Eko, 19 l’Ogun, 3 ní Nassarawa

Oríṣun àwòrán, Getty Images
O n bọ o n bọ, amojuto ati igbaradi ti yoo dena rẹ ni aye n dẹ de e bayii.
Eyi wa ni ibamu pẹlu bi ajọ to n ri si iṣẹlẹ pajawiri lorilẹede Naijiria, National Emergency Management Agency (NEMA), ṣe n kilọ pe isẹlẹ ẹkun omi yoo ṣọṣẹ ni awọn agbegbe ijọba ibilẹ kan nipinlẹ Eko ati Ogun.
NEMA ninu ikilọ tuntun naa sọ pe bi ojo ba ṣe n rọ, to si n pọ ni awọn agbegbe wọnyi wa ninu ewu omiyale.
Agbegbe mẹẹẹdogun (15) ni NEMA kilọ nipa rẹ l'Eko, mọkandinlogun (19), ni wọn kilọ pe ki wọn ṣọra nipinlẹ Ogun, eyi to mu apapọ wọn jẹ mẹrinlọgbọn (34).
Awọn ikilọ ewu ẹkun omi to seese ko waye ni ipinlẹ mẹta nilẹ Naijiria ni ajọ NEMA fi si oju opo X rẹ, @nemanigeria lọjọ Iṣẹgun.

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Wọnyi ni awọn agbegbe ijọba ibilẹ ti ọrọ naa kan l'Eko
Agege
Alimosho
Ikeja
Kosofe
Ikorodu
Lagos Island
Eti-Osa
Amuwo-Odofin
Apapa
Badagry
Epe
Ibeju-Lekki
Ajeromi-Ifelodun
Ifako-Ijaiye ati
Lagos Mainland.

Oríṣun àwòrán, @nemanigeria
Awọn ijọba ibilẹ to wa ninu ewu ẹkun omi l'Ogun
Abeokuta North
Abeokuta South
Ado-Odo/Ota
Ifo
Sagamu
Ijebu Ode
Obafemi Owode
Ewekoro
Odogbolu
Yewa North
Yewa South
Imeko Afon
Ipokia
Awọn yoku l'Ogun ni:
Odeda
Ikenne
Remo North
Ijebu East
Ijebu North ati
Ijebu North East.

Oríṣun àwòrán, @nemanigeria
Ijọba ibilẹ mẹta lo wa ninu ewu ẹkun omi ni ipinlẹ Nassarawa
Ijọba ibilẹ Nassarawa
Ijọba ibilẹ Doma
Ijọba ibilẹ Toto

Oríṣun àwòrán, @nemanigeria

Wo ohun ti ajọ NEMA ni ki o se lati dena ẹkun omi to n bọ
NEMA ni kawọn to ba n gbe ni bebe okun lagbegbe naa tete fi ibẹ silẹ, awọn to si n gbe lori ilẹ gbigbẹ naa gbọdọ tete ko awọn koto idaminu wọn daadaa pẹlu bi wọn ṣe sọ.
Wọn fi kun un pe ikilọ yii n waye lẹyin ti ajọ to n ri si oju ọjọ ti kede pe o ṣee ṣe ki ojo ti yoo maa rọ bayii maa pọ si I ju ti tẹlẹ lọ.
Eyi ni wọn lo le fa omiyale lawọn agbegbe ti anfaani idominu geere ko ba si fun wọn, ti wọn ko si tete mojuto o.


























